Surah An-Noor Verse 2 - Yoruba Translation by Shaykh Abu Rahimah Mikael Aykyuni
Surah An-Noorٱلزَّانِيَةُ وَٱلزَّانِي فَٱجۡلِدُواْ كُلَّ وَٰحِدٖ مِّنۡهُمَا مِاْئَةَ جَلۡدَةٖۖ وَلَا تَأۡخُذۡكُم بِهِمَا رَأۡفَةٞ فِي دِينِ ٱللَّهِ إِن كُنتُمۡ تُؤۡمِنُونَ بِٱللَّهِ وَٱلۡيَوۡمِ ٱلۡأٓخِرِۖ وَلۡيَشۡهَدۡ عَذَابَهُمَا طَآئِفَةٞ مِّنَ ٱلۡمُؤۡمِنِينَ
Onísìná lóbìnrin àti onísìná lọ́kùnrin, ẹ na ẹnìkọ̀ọ̀kan nínú àwọn méjèèjì ní ọgọ́rùn-ún kòbókò. Ẹ má ṣe jẹ́ kí àánú wọn ṣe yín nípa ìdájọ́ Allāhu tí ẹ bá ní ìgbàgbọ́ òdodo nínú Allāhu àti Ọjọ́ Ìkẹ́yìn. Kí igun kan nínú àwọn onígbàgbọ́ òdodo sì jẹ́rìí sí ìyà àwọn méjèèjì. tí ó bá di oyún tí ọkọ rẹ̀ kò sì mọ̀ wọn kò níí fún wọn lẹ́tọ̀ọ́ sí oorun ìfẹ́ mìíràn mọ́ torí pé kò sí ìtakókó yìgì láààrin wọn. Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé a rí nínú àwọn onímọ̀ ẹ̀sìn t’ó ní wọ́n lè ṣe ìtakókó yìgì obìnrin náà fún arákùnrin t’ó ṣe zinā pẹ̀lú rẹ̀ lórí oyún zinā náà nítorí kí wọ́n lè máa jẹ ìgbádùn ara wọn lọ ní ọ̀nà ẹ̀tọ́ èyí tí ó dára jùlọ ni pé